1 Kronika 3:1-4
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Àwọn ọmọ Dafidi
3 (A)Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Dafidi tí a bí fún un ní Hebroni:
Àkọ́bí sì ni Amnoni ọmọ Ahinoamu ti Jesreeli;
èkejì sì ni Daniẹli ọmọ Abigaili ará Karmeli;
2 Ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un;
ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti;
3 Ẹ̀karùnún ni Ṣefatia láti ọ̀dọ̀ Abitali;
àti ẹ̀kẹfà, Itreamu, láti ọ̀dọ̀ Egla aya rẹ̀.
4 (B)Àwọn mẹ́fà wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni, níbi tí ó ti jẹ ọba fún ọdún méje àti oṣù mẹ́fà.
Dafidi sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n (33).
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.