Add parallel Print Page Options

Ẹ̀ka láti ọ̀dọ̀ Jese

11 (A)Èèkàn kan yóò sọ láti ibi
    kùkùté Jese,
láti ara gbòǹgbò rẹ̀ ni ẹ̀ka kan
    yóò ti so èso.
(B)Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé e
    ẹ̀mí ọgbọ́n àti ti òye
ẹ̀mí ìmọ̀ràn àti ti agbára
    ẹ̀mí ìmọ̀ àti ti ìbẹ̀rù Olúwa
Òun yóò sì ní inú dídùn nínú ìbẹ̀rù Olúwa.

    Òun kì yóò ṣe ìdájọ́ pẹ̀lú ohun tí ó fi ojú u rẹ̀ rí,
    tàbí pẹ̀lú ohun tí ó fi etí i rẹ̀ gbọ́,
Ṣùgbọ́n pẹ̀lú òdodo ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní,
    pẹ̀lú òtítọ́ ni yóò ṣe ìpinnu
fún àwọn aláìní ayé.
    Òun yóò lu ayé pẹ̀lú ọ̀pá tí ó wà ní ẹnu rẹ̀,
    pẹ̀lú èémí ẹnu rẹ̀ ni yóò pa àwọn ìkà.
(C)Òdodo ni yóò jẹ́ ìgbànú rẹ̀
    àti òtítọ́ ni yóò ṣe ọ̀já yí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ká.

(D)Ìkookò yóò sì máa bá ọmọ àgùntàn gbé,
    ẹkùn yóò sì sùn ti ewúrẹ́
ọmọ màlúù òun ọmọ kìnnìún
    àti ọmọ ẹran ó wà papọ̀
    ọ̀dọ́mọdé yóò sì máa dà wọ́n.
Màlúù àti beari yóò máa jẹun pọ̀,
    àwọn ọmọ wọn yóò dùbúlẹ̀ pọ̀,
kìnnìún yóò sì máa jẹ koríko
    gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù.
Ọ̀dọ́mọdé yóò ṣeré lẹ́bàá ihò ọká,
    ọmọdé yóò ki ọwọ́ rẹ̀ bọ ìtẹ́ paramọ́lẹ̀.
Wọn kò ní ṣe ni léṣe tàbí pa ni run
    ní gbogbo òkè mímọ́ mi,
nítorí gbogbo ayé yóò kún fún ìmọ̀ Olúwa
    gẹ́gẹ́ bí omi ti bo Òkun.

10 (E)Ní ọjọ́ náà, gbòǹgbò Jese yóò dúró gẹ́gẹ́ bí àsíá fún gbogbo ènìyàn, àwọn orílẹ̀-èdè yóò pagbo yí i ká, ibùdó ìsinmi rẹ̀ yóò jẹ́ èyí tí ó lógo. 11 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò na ọwọ́ rẹ̀ jáde nígbà kejì láti tún gba àwọn tí ó ṣẹ́kù àní àwọn tí a ṣẹ́kù nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ láti Asiria wá, láti ìsàlẹ̀ Ejibiti àti Òkè Ejibiti, láti Kuṣi, láti Elamu láti Babiloni, láti Hamati àti láti àwọn erékùṣù inú Òkun.

12 Òun yóò gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè,
    yóò sì kó àwọn ìgbèkùn Israẹli jọ,
yóò kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí a ti fọ́n káàkiri jọ,
    láti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ ayé.
13 Owú jíjẹ Efraimu yóò pòórá,
    àwọn ọ̀tá Juda ni a ó ké kúrò,
Efraimu kò ní jowú Juda,
    tàbí Juda kó dojúkọ Efraimu.
14 Wọn yóò fò mọ́ èjìká Filistini
    sí apá ìwọ̀-oòrùn,
wọn yóò pawọ́pọ̀ kọlu àwọn
    ènìyàn apá ìlà-oòrùn.
Wọn yóò gbé ọwọ́ wọn lé Edomu àti Moabu,
    àwọn ará Ammoni yóò sì di ìwẹ̀fà wọn.
15 Olúwa yóò sọ di gbígbé
    àyasí Òkun Ejibiti,
pẹ̀lú atẹ́gùn gbígbóná ni yóò na ọwọ́ rẹ̀,
    kọjá lórí odò Eufurate.
Òun yóò sì sọ ọ́ di ọmọdò méje
    tó fi jẹ́ pé àwọn ènìyàn
    yóò máa là á kọjá pẹ̀lú bàtà.
16 Ọ̀nà gidi yóò wà fún àwọn ènìyàn an rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù
    tí ó kù sílẹ̀ ní Asiria,
gẹ́gẹ́ bí ó ti wà fún Israẹli
    nígbà tí wọ́n gòkè láti Ejibiti wá.

The Branch From Jesse

11 A shoot(A) will come up from the stump(B) of Jesse;(C)
    from his roots a Branch(D) will bear fruit.(E)
The Spirit(F) of the Lord will rest on him—
    the Spirit of wisdom(G) and of understanding,
    the Spirit of counsel and of might,(H)
    the Spirit of the knowledge and fear of the Lord
and he will delight in the fear(I) of the Lord.

He will not judge by what he sees with his eyes,(J)
    or decide by what he hears with his ears;(K)
but with righteousness(L) he will judge the needy,(M)
    with justice(N) he will give decisions for the poor(O) of the earth.
He will strike(P) the earth with the rod of his mouth;(Q)
    with the breath(R) of his lips he will slay the wicked.(S)
Righteousness will be his belt(T)
    and faithfulness(U) the sash around his waist.(V)

The wolf will live with the lamb,(W)
    the leopard will lie down with the goat,
the calf and the lion and the yearling[a] together;
    and a little child will lead them.
The cow will feed with the bear,
    their young will lie down together,
    and the lion will eat straw like the ox.(X)
The infant(Y) will play near the cobra’s den,
    and the young child will put its hand into the viper’s(Z) nest.
They will neither harm nor destroy(AA)
    on all my holy mountain,(AB)
for the earth(AC) will be filled with the knowledge(AD) of the Lord
    as the waters cover the sea.

10 In that day(AE) the Root of Jesse(AF) will stand as a banner(AG) for the peoples; the nations(AH) will rally to him,(AI) and his resting place(AJ) will be glorious.(AK) 11 In that day(AL) the Lord will reach out his hand a second time to reclaim the surviving remnant(AM) of his people from Assyria,(AN) from Lower Egypt, from Upper Egypt,(AO) from Cush,[b](AP) from Elam,(AQ) from Babylonia,[c] from Hamath(AR) and from the islands(AS) of the Mediterranean.(AT)

12 He will raise a banner(AU) for the nations
    and gather(AV) the exiles of Israel;(AW)
he will assemble the scattered people(AX) of Judah
    from the four quarters of the earth.(AY)
13 Ephraim’s jealousy will vanish,
    and Judah’s enemies[d] will be destroyed;
Ephraim will not be jealous of Judah,
    nor Judah hostile toward Ephraim.(AZ)
14 They will swoop down on the slopes of Philistia(BA) to the west;
    together they will plunder the people to the east.(BB)
They will subdue Edom(BC) and Moab,(BD)
    and the Ammonites(BE) will be subject to them.(BF)
15 The Lord will dry up(BG)
    the gulf of the Egyptian sea;
with a scorching wind(BH) he will sweep his hand(BI)
    over the Euphrates River.(BJ)
He will break it up into seven streams
    so that anyone can cross over in sandals.(BK)
16 There will be a highway(BL) for the remnant(BM) of his people
    that is left from Assyria,(BN)
as there was for Israel
    when they came up from Egypt.(BO)

Footnotes

  1. Isaiah 11:6 Hebrew; Septuagint lion will feed
  2. Isaiah 11:11 That is, the upper Nile region
  3. Isaiah 11:11 Hebrew Shinar
  4. Isaiah 11:13 Or hostility