Add parallel Print Page Options

Jobu gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run

13 “Wò ó, ojú mi ti rí gbogbo èyí rí,
    etí mí sì gbọ́, ó sì ti yé mi.
Ohun tí ẹ̀yin mọ̀, èmi mọ̀ pẹ̀lú,
    èmi kò kéré sí i yin.
Nítòótọ́ èmi ó bá Olódùmarè
    sọ̀rọ̀, èmi sì ń fẹ́ bá Ọlọ́run sọ àsọyé.
Ẹ̀yin fi irọ́ bá mi sọ̀rọ̀,
    oníṣègùn lásán ni gbogbo yín.
Háà! ẹ̀yin kì bá kúkú dákẹ́!
    Èyí ni kì bá sì ṣe ọgbọ́n yín.
Ẹ gbọ́ àwíyé mi nísinsin yìí;
    ẹ sì fetísílẹ̀ sí àròyé ẹnu mi.
Ẹ̀yin fẹ́ sọ ìsọkúsọ fún Ọlọ́run?
    Ki ẹ sì fi ẹ̀tàn sọ̀rọ̀ gbè é?
Ẹ̀yin fẹ́ ṣe ojúsàájú rẹ̀?
    Ẹ̀yin fẹ́ gbèjà fún Ọlọ́run?
Ó ha dára to tí yóò hú àṣírí yín síta,
    Tàbí kí ẹ̀yin tàn án bí ẹnìkan ti í tan ẹnìkejì?
10 Yóò máa bá yín wí nítòótọ́,
    bí ẹ̀yin bá ṣe ojúsàájú ènìyàn níkọ̀kọ̀.
11 Ìwà ọlá rẹ̀ kì yóò bà yín lẹ́rù bí?
    Ìpayà rẹ̀ kì yóò pá yín láyà?
12 Àwọn òwe yín dàbí eérú;
    Bẹ́ẹ̀ ni àwọn odi ìlú yin dàbí amọ̀.

13 “Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi, kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀,
    ki ohun tí ń bọ̀ wá í bá mi, le è máa bọ̀.
14 Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi eyín mi bu ẹran-ara mi jẹ,
    Tí mo sì gbé ẹ̀mí mi lé ara mi lọ́wọ́?
15 Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e;
    Ṣùgbọ́n èmi ó máa tẹnumọ́ ọ̀nà mi níwájú rẹ̀.
16 Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi,
    Àgàbàgebè kì yóò wá síwájú rẹ̀.
17 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfarabalẹ̀,
    jẹ́ kí ọ̀rọ̀ mí dún ni etí yín.
18 Wò ó nísinsin yìí, èmi ti mura ọ̀ràn mi sílẹ̀;
    èmi mọ̀ pé a ó dá mi láre.
19 Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé?
    Ǹjẹ́ nísinsin yìí, èmi fẹ́ pa ẹnu mi mọ́,
    èmi ó sì jọ̀wọ́ ẹ̀mí mi lọ́wọ́.

20 “Ṣùgbọ́n, má ṣe ṣe ohun méjì yìí sí mi,
    Nígbà náà ni èmi kì yóò sì fi ara mi pamọ́ kúrò fún ọ:
21 Fa ọwọ́ rẹ sẹ́yìn kúrò lára mi,
    má sì jẹ́ kí ẹ̀rù rẹ kí ó pá mi láyà.
22 Nígbà náà ni kí ìwọ kí ó pè, èmi o sì dáhùn;
    Ta ni jẹ́ kí ń máa sọ̀rọ̀, ki ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
23 Mélòó ní àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ mi?
    Mú mi mọ̀ ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ mi.
24 Nítorí kí ni ìwọ ṣe pa ojú rẹ mọ́,
    tí o sì yàn mí ní ọ̀tá rẹ?
25 Ìwọ ó fa ewé ti afẹ́fẹ́ ń fẹ́ síhìn-ín sọ́hùn-ún ya bi?
    Ìwọ a sì máa lépa ìyàngbò?
26 Nítorí pé ìwọ kọ̀wé ohun kíkorò sí mi,
    o sì mú mi jogún àìṣedéédéé èwe mi.
27 Ìwọ kàn àbà mọ́ mi lẹ́sẹ̀ pẹ̀lú,
    ìwọ sì ń wò ipa ọ̀nà ìrìn mi ní àwòfín;
    nípa fífi ìlà yí gígísẹ̀ mi ká.

28 “Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn ń ṣègbé bí ohun ìdíbàjẹ́,
    Bi aṣọ tí kòkòrò jẹ.

13 “My eyes have seen all this,(A)
    my ears have heard and understood it.
What you know, I also know;
    I am not inferior to you.(B)
But I desire to speak to the Almighty(C)
    and to argue my case with God.(D)
You, however, smear me with lies;(E)
    you are worthless physicians,(F) all of you!(G)
If only you would be altogether silent!(H)
    For you, that would be wisdom.(I)
Hear now my argument;
    listen to the pleas of my lips.(J)
Will you speak wickedly on God’s behalf?
    Will you speak deceitfully for him?(K)
Will you show him partiality?(L)
    Will you argue the case for God?
Would it turn out well if he examined you?(M)
    Could you deceive him as you might deceive a mortal?(N)
10 He would surely call you to account
    if you secretly showed partiality.(O)
11 Would not his splendor(P) terrify you?
    Would not the dread of him fall on you?(Q)
12 Your maxims are proverbs of ashes;
    your defenses are defenses of clay.(R)

13 “Keep silent(S) and let me speak;(T)
    then let come to me what may.(U)
14 Why do I put myself in jeopardy
    and take my life in my hands?(V)
15 Though he slay me, yet will I hope(W) in him;(X)
    I will surely[a] defend my ways to his face.(Y)
16 Indeed, this will turn out for my deliverance,(Z)
    for no godless(AA) person would dare come before him!(AB)
17 Listen carefully to what I say;(AC)
    let my words ring in your ears.
18 Now that I have prepared my case,(AD)
    I know I will be vindicated.(AE)
19 Can anyone bring charges against me?(AF)
    If so, I will be silent(AG) and die.(AH)

20 “Only grant me these two things, God,
    and then I will not hide from you:
21 Withdraw your hand(AI) far from me,
    and stop frightening me with your terrors.(AJ)
22 Then summon me and I will answer,(AK)
    or let me speak, and you reply to me.(AL)
23 How many wrongs and sins have I committed?(AM)
    Show me my offense and my sin.(AN)
24 Why do you hide your face(AO)
    and consider me your enemy?(AP)
25 Will you torment(AQ) a windblown leaf?(AR)
    Will you chase(AS) after dry chaff?(AT)
26 For you write down bitter things against me
    and make me reap the sins of my youth.(AU)
27 You fasten my feet in shackles;(AV)
    you keep close watch on all my paths(AW)
    by putting marks on the soles of my feet.

28 “So man wastes away like something rotten,
    like a garment(AX) eaten by moths.(AY)

Footnotes

  1. Job 13:15 Or He will surely slay me; I have no hope — / yet I will