Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa.

59 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run;
    dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú
    kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.

Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí!
    Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi
Kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí.
    Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Olúwa Ọlọ́run Alágbára,
    Ọlọ́run Israẹli,
dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí;
    má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. Sela.

Wọ́n padà ní àṣálẹ́,
    wọ́n ń gbó bí àwọn ajá,
    wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu:
    wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn,
    wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín
    Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.

Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ;
    nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
10     Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi.

Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi.
    Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa,
    kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé.
Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri,
    kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn,
    ní ọ̀rọ̀ ètè wọn,
    kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn.
Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
13     Pa wọ́n run nínú ìbínú,
    run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́.
Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé
    pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. Sela.

14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́,
    wọn ń gbó bí àwọn ajá
    wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ
    wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ,
    n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀;
nítorí ìwọ ni ààbò mi,
    ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.

17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ;
    ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.

Psalm 59[a]

For the director of music. To the tune of “Do Not Destroy.” Of David. A miktam.[b] When Saul had sent men to watch David’s house(A) in order to kill him.

Deliver me from my enemies, O God;(B)
    be my fortress against those who are attacking me.(C)
Deliver me from evildoers(D)
    and save me from those who are after my blood.(E)

See how they lie in wait for me!
    Fierce men conspire(F) against me
    for no offense or sin of mine, Lord.
I have done no wrong,(G) yet they are ready to attack me.(H)
    Arise to help me; look on my plight!(I)
You, Lord God Almighty,
    you who are the God of Israel,(J)
rouse yourself(K) to punish all the nations;(L)
    show no mercy to wicked traitors.[c](M)

They return at evening,
    snarling like dogs,(N)
    and prowl about the city.
See what they spew from their mouths(O)
    the words from their lips are sharp as swords,(P)
    and they think, “Who can hear us?”(Q)
But you laugh at them, Lord;(R)
    you scoff at all those nations.(S)

You are my strength,(T) I watch for you;
    you, God, are my fortress,(U)
10     my God on whom I can rely.

God will go before me
    and will let me gloat over those who slander me.
11 But do not kill them, Lord our shield,[d](V)
    or my people will forget.(W)
In your might uproot them
    and bring them down.(X)
12 For the sins of their mouths,(Y)
    for the words of their lips,(Z)
    let them be caught in their pride.(AA)
For the curses and lies they utter,
13     consume them in your wrath,
    consume them till they are no more.(AB)
Then it will be known to the ends of the earth
    that God rules over Jacob.(AC)

14 They return at evening,
    snarling like dogs,
    and prowl about the city.
15 They wander about for food(AD)
    and howl if not satisfied.
16 But I will sing(AE) of your strength,(AF)
    in the morning(AG) I will sing of your love;(AH)
for you are my fortress,(AI)
    my refuge in times of trouble.(AJ)

17 You are my strength, I sing praise to you;
    you, God, are my fortress,
    my God on whom I can rely.(AK)

Footnotes

  1. Psalm 59:1 In Hebrew texts 59:1-17 is numbered 59:2-18.
  2. Psalm 59:1 Title: Probably a literary or musical term
  3. Psalm 59:5 The Hebrew has Selah (a word of uncertain meaning) here and at the end of verse 13.
  4. Psalm 59:11 Or sovereign